Add parallel Print Page Options

Kaini àti Abeli

Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.” Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli.

Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀. Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀. (A)Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.

Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro? Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”

(B)Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.

Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?”

Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”

10 Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá. 11 Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ. 12 Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”

13 Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ. 14 Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”

15 Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi ààmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á. 16 Kaini sì kúrò níwájú Ọlọ́run, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.

17 Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà. 18 Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.

19 Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla. 20 Adah sì bí Jabali: òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn. 21 Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè. 22 Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.

23 Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀,

“Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi;
    ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí,
    ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24 Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje,
    ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tà-dínlọ́gọ́rin.”

25 Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.” 26 Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi.

Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

Cain and Abel

Adam[a] made love to his wife(A) Eve,(B) and she became pregnant and gave birth to Cain.[b](C) She said, “With the help of the Lord I have brought forth[c] a man.” Later she gave birth to his brother Abel.(D)

Now Abel kept flocks, and Cain worked the soil.(E) In the course of time Cain brought some of the fruits of the soil as an offering(F) to the Lord.(G) And Abel also brought an offering—fat portions(H) from some of the firstborn of his flock.(I) The Lord looked with favor on Abel and his offering,(J) but on Cain and his offering he did not look with favor. So Cain was very angry, and his face was downcast.

Then the Lord said to Cain, “Why are you angry?(K) Why is your face downcast? If you do what is right, will you not be accepted? But if you do not do what is right, sin is crouching at your door;(L) it desires to have you, but you must rule over it.(M)

Now Cain said to his brother Abel, “Let’s go out to the field.”[d] While they were in the field, Cain attacked his brother Abel and killed him.(N)

Then the Lord said to Cain, “Where is your brother Abel?”(O)

“I don’t know,(P)” he replied. “Am I my brother’s keeper?”

10 The Lord said, “What have you done? Listen! Your brother’s blood cries out to me from the ground.(Q) 11 Now you are under a curse(R) and driven from the ground, which opened its mouth to receive your brother’s blood from your hand. 12 When you work the ground, it will no longer yield its crops for you.(S) You will be a restless wanderer(T) on the earth.(U)

13 Cain said to the Lord, “My punishment is more than I can bear. 14 Today you are driving me from the land, and I will be hidden from your presence;(V) I will be a restless wanderer on the earth,(W) and whoever finds me will kill me.”(X)

15 But the Lord said to him, “Not so[e]; anyone who kills Cain(Y) will suffer vengeance(Z) seven times over.(AA)” Then the Lord put a mark on Cain so that no one who found him would kill him. 16 So Cain went out from the Lord’s presence(AB) and lived in the land of Nod,[f] east of Eden.(AC)

17 Cain made love to his wife,(AD) and she became pregnant and gave birth to Enoch. Cain was then building a city,(AE) and he named it after his son(AF) Enoch. 18 To Enoch was born Irad, and Irad was the father of Mehujael, and Mehujael was the father of Methushael, and Methushael was the father of Lamech.

19 Lamech married(AG) two women,(AH) one named Adah and the other Zillah. 20 Adah gave birth to Jabal; he was the father of those who live in tents and raise livestock. 21 His brother’s name was Jubal; he was the father of all who play stringed instruments(AI) and pipes.(AJ) 22 Zillah also had a son, Tubal-Cain, who forged(AK) all kinds of tools out of[g] bronze and iron. Tubal-Cain’s sister was Naamah.

23 Lamech said to his wives,

“Adah and Zillah, listen to me;
    wives of Lamech, hear my words.
I have killed(AL) a man for wounding me,
    a young man for injuring me.
24 If Cain is avenged(AM) seven times,(AN)
    then Lamech seventy-seven times.(AO)

25 Adam made love to his wife(AP) again, and she gave birth to a son and named him Seth,[h](AQ) saying, “God has granted me another child in place of Abel, since Cain killed him.”(AR) 26 Seth also had a son, and he named him Enosh.(AS)

At that time people began to call on[i] the name of the Lord.(AT)

Footnotes

  1. Genesis 4:1 Or The man
  2. Genesis 4:1 Cain sounds like the Hebrew for brought forth or acquired.
  3. Genesis 4:1 Or have acquired
  4. Genesis 4:8 Samaritan Pentateuch, Septuagint, Vulgate and Syriac; Masoretic Text does not have “Let’s go out to the field.”
  5. Genesis 4:15 Septuagint, Vulgate and Syriac; Hebrew Very well
  6. Genesis 4:16 Nod means wandering (see verses 12 and 14).
  7. Genesis 4:22 Or who instructed all who work in
  8. Genesis 4:25 Seth probably means granted.
  9. Genesis 4:26 Or to proclaim