Add parallel Print Page Options

Àdúrà Jona

Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá, Ó sì wí pé:

“Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa,
    òun sì gbọ́ ohùn mi.
Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́,
    ìwọ sì gbọ́ ohùn mi.
Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú,
    ní àárín Òkun,
    ìṣàn omi sì yí mi káàkiri;
gbogbo bíbì omi àti rírú omi
    rékọjá lórí mi.
Nígbà náà ni mo wí pé,
    ‘a ta mí nù kúrò níwájú rẹ;
ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún
    máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn;
    ibú yí mi káàkiri,
    a fi koríko odò wé mi lórí.
Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá;
    ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí:
ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá,
    Olúwa Ọlọ́run mi.

“Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi,
    èmi rántí rẹ, Olúwa,
àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,
    nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.

“Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké
    kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ.
    Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́.
    ‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’ ”

10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.

[a]From inside the fish Jonah prayed to the Lord his God. He said:

“In my distress I called(A) to the Lord,(B)
    and he answered me.
From deep in the realm of the dead(C) I called for help,
    and you listened to my cry.
You hurled me into the depths,(D)
    into the very heart of the seas,
    and the currents swirled about me;
all your waves(E) and breakers
    swept over me.(F)
I said, ‘I have been banished
    from your sight;(G)
yet I will look again
    toward your holy temple.’(H)
The engulfing waters threatened me,[b]
    the deep surrounded me;
    seaweed was wrapped around my head.(I)
To the roots of the mountains(J) I sank down;
    the earth beneath barred me in forever.
But you, Lord my God,
    brought my life up from the pit.(K)

“When my life was ebbing away,
    I remembered(L) you, Lord,
and my prayer(M) rose to you,
    to your holy temple.(N)

“Those who cling to worthless idols(O)
    turn away from God’s love for them.
But I, with shouts of grateful praise,(P)
    will sacrifice(Q) to you.
What I have vowed(R) I will make good.
    I will say, ‘Salvation(S) comes from the Lord.’”

10 And the Lord commanded the fish, and it vomited Jonah onto dry land.

Footnotes

  1. Jonah 2:1 In Hebrew texts 2:1 is numbered 1:17, and 2:1-10 is numbered 2:2-11.
  2. Jonah 2:5 Or waters were at my throat