Add parallel Print Page Options

Orin fún ìgòkè.

132 Olúwa, rántí Dafidi
    nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.

Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa,
    tí ó sì ṣe ìlérí fún Alágbára Jakọbu pé.
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ,
    bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi:
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi,
    tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
Títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa,
    ibùjókòó fún Alágbára Jakọbu.

Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata:
    àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀:
    àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ:
    ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ:
    kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.

10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀
    Má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.

11 (A)Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi:
    Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀,
    nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́
    àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn,
    àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.

13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni:
    ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé:
    níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé:
    nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀:
    èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀:
    àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.

17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀,
    èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀:
    ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.

Psalm 132(A)

A song of ascents.

Lord, remember David
    and all his self-denial.(B)

He swore an oath to the Lord,
    he made a vow to the Mighty One of Jacob:(C)
“I will not enter my house(D)
    or go to my bed,
I will allow no sleep to my eyes
    or slumber to my eyelids,
till I find a place(E) for the Lord,
    a dwelling for the Mighty One of Jacob.”

We heard it in Ephrathah,(F)
    we came upon it in the fields of Jaar:[a](G)
“Let us go to his dwelling place,(H)
    let us worship at his footstool,(I) saying,
‘Arise, Lord,(J) and come to your resting place,
    you and the ark of your might.
May your priests be clothed with your righteousness;(K)
    may your faithful people(L) sing for joy.’”

10 For the sake of your servant David,
    do not reject your anointed one.

11 The Lord swore an oath to David,(M)
    a sure oath he will not revoke:
“One of your own descendants(N)
    I will place on your throne.
12 If your sons keep my covenant(O)
    and the statutes I teach them,
then their sons will sit
    on your throne(P) for ever and ever.”

13 For the Lord has chosen Zion,(Q)
    he has desired it for his dwelling,(R) saying,
14 “This is my resting place for ever and ever;(S)
    here I will sit enthroned,(T) for I have desired it.
15 I will bless her with abundant provisions;
    her poor I will satisfy with food.(U)
16 I will clothe her priests(V) with salvation,
    and her faithful people will ever sing for joy.(W)

17 “Here I will make a horn[b] grow(X) for David
    and set up a lamp(Y) for my anointed one.(Z)
18 I will clothe his enemies with shame,(AA)
    but his head will be adorned with a radiant crown.”(AB)

Footnotes

  1. Psalm 132:6 Or heard of it in Ephrathah, / we found it in the fields of Jearim. (See 1 Chron. 13:5,6) (And no quotation marks around verses 7-9)
  2. Psalm 132:17 Horn here symbolizes strong one, that is, king.